Prev  

70. Surah Al-Ma'ârij سورة المعارج

  Next  




1st Ayah  1  الأية ١الأولي
بِسْم ِ اللهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ
سَأَلَ سَائِلٌ بِعَذَابٍ وَاقِعٍ
Saala sa-ilun biAAathabin waqiAA

Yoruba
 
Oníbèéèrè kan bèèrè nípa ìyà tó máa ṣẹlẹ̀

Ayah  70:2  الأية
لِّلْكَافِرِينَ لَيْسَ لَهُ دَافِعٌ
Lilkafireena laysa lahu dafiAA

Yoruba
 
Sí àwọn aláìgbàgbọ́. Kò sì sí ẹni tí ó máa dí i lọ́wọ́

Ayah  70:3  الأية
مِّنَ اللهِ ذِي الْمَعَارِجِ
Mina Allahi thee almaAAarij

Yoruba
 
Lọ́dọ̀ Allāhu, Onípò-àyè gíga.

Ayah  70:4  الأية
تَعْرُجُ الْمَلَائِكَةُ وَالرُّوحُ إِلَيْهِ فِي يَوْمٍ كَانَ مِقْدَارُهُ خَمْسِينَ أَلْفَ سَنَةٍ
TaAAruju almala-ikatu warroohuilayhi fee yawmin kana miqdaruhu khamseena alfasana

Yoruba
 
Àwọn mọlāika àti mọlāika Jibrīl ń gùnkè wá sí ọ̀dọ̀ Rẹ̀ nínú ọjọ́ kan tí òdiwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ààbọ̀ ọdún (tí ẹ bá fẹ́ rìn ín).

Ayah  70:5  الأية
فَاصْبِرْ صَبْرًا جَمِيلًا
Fasbir sabran jameela

Yoruba
 
Nítorí náà, ṣe sùúrù ní sùúrù tó rẹwà.

Ayah  70:6  الأية
إِنَّهُمْ يَرَوْنَهُ بَعِيدًا
Innahum yarawnahu baAAeeda

Yoruba
 
Dájúdájú wọ́n ń wo (ìyà náà) ní ohun tó jìnnà.

Ayah  70:7  الأية
وَنَرَاهُ قَرِيبًا
Wanarahu qareeba

Yoruba
 
A sì ń wò ó ní ohun tó súnmọ́.

Ayah  70:8  الأية
يَوْمَ تَكُونُ السَّمَاءُ كَالْمُهْلِ
Yawma takoonu assamao kalmuhl

Yoruba
 
(Ọjọ́ náà ni) ọjọ́ tí sánmọ̀ yó dà bí ògéré epo gbígbóná,

Ayah  70:9  الأية
وَتَكُونُ الْجِبَالُ كَالْعِهْنِ
Watakoonu aljibalu kalAAihn

Yoruba
 
Àwọn àpáta yó sì dà bí ẹ̀gbọ̀n òwú-irun,

Ayah  70:10  الأية
وَلَا يَسْأَلُ حَمِيمٌ حَمِيمًا
Wala yas-alu hameemun hameema

Yoruba
 
ọ̀rẹ́ ìmùlẹ̀ kan kò sì níí bèèrè ọ̀rẹ́ ìmùlẹ̀ (rẹ̀).

Ayah  70:11  الأية
يُبَصَّرُونَهُمْ ۚ يَوَدُّ الْمُجْرِمُ لَوْ يَفْتَدِي مِنْ عَذَابِ يَوْمِئِذٍ بِبَنِيهِ
Yubassaroonahum yawaddu almujrimu lawyaftadee min AAathabi yawmi-ithin bibaneeh

Yoruba
 
Wọ́n máa rí ara wọn (wọ́n sì máa dára wọn mọ̀). Ẹlẹ́ṣẹ̀ sì máa fẹ́ kí òun fi àwọn ọmọ rẹ̀ ṣèràpadà ẹ̀mí ara rẹ̀ níbi Ìyà ní ọjọ́ yẹn.

Ayah  70:12  الأية
وَصَاحِبَتِهِ وَأَخِيهِ
Wasahibatihi waakheeh

Yoruba
 
Ìyàwó rẹ̀ àti arákùnrin rẹ̀,

Ayah  70:13  الأية
وَفَصِيلَتِهِ الَّتِي تُؤْوِيهِ
Wafaseelatihi allatee tu/weeh

Yoruba
 
Àti àwọn ẹbí rẹ̀ tó pa tì, tí àwọn sì ń gbà á sọ́dọ̀ nílé ayé,

Ayah  70:14  الأية
وَمَن فِي الْأَرْضِ جَمِيعًا ثُمَّ يُنجِيهِ
Waman fee al-ardi jameeAAan thummayunjeeh

Yoruba
 
Àti gbogbo ẹni tó wà lórí ilẹ̀ ayé pátápátá, (ó máa fẹ́ fi wọ́n ṣèràpadà ẹ̀mí ara rẹ̀ níbi Ìyà). Lẹ́yìn náà, (ó máa fẹ́) kí Allāhu gba òun là (nínú ìyà Iná).

Ayah  70:15  الأية
كَلَّا ۖ إِنَّهَا لَظَىٰ
Kalla innaha latha

Yoruba
 
Rárá! Dájúdájú (ó máa wọ) iná Laṭḥọ̄ (iná tó ń jò fòfò).

Ayah  70:16  الأية
نَزَّاعَةً لِّلشَّوَىٰ
NazzaAAatan lishshawa

Yoruba
 
Ó máa bó awọ orí tòró.

Ayah  70:17  الأية
تَدْعُو مَنْ أَدْبَرَ وَتَوَلَّىٰ
TadAAoo man adbara watawalla

Yoruba
 
(Iná) yó máa ké sí ẹni tó kẹ̀yìn sí (ìgbágbọ́ òdodo), tí ó sì takété sí i,

Ayah  70:18  الأية
وَجَمَعَ فَأَوْعَىٰ
WajamaAAa faawAAa

Yoruba
 
Ó kó (ọrọ̀) jọ, ó sì fi pamọ́ (kò ná an fún ẹ̀sìn).

Ayah  70:19  الأية
إِنَّ الْإِنسَانَ خُلِقَ هَلُوعًا
Inna al-insana khuliqa halooAAa

Yoruba
 
Dájúdájú ènìyàn, A ṣẹ̀dá rẹ̀ ní aláìlọ́kàn, ọ̀kánjúà.

Ayah  70:20  الأية
إِذَا مَسَّهُ الشَّرُّ جَزُوعًا
Itha massahu ashsharrujazooAAa

Yoruba
 
Nígbà tí aburú bá fọwọ́ bà á, ó máa kanra gógó.

Ayah  70:21  الأية
وَإِذَا مَسَّهُ الْخَيْرُ مَنُوعًا
Wa-itha massahu alkhayru manooAAa

Yoruba
 
Nígbà tí ọwọ́ rẹ̀ bá sì ba oore, ó máa yahun.

Ayah  70:22  الأية
إِلَّا الْمُصَلِّينَ
Illa almusalleen

Yoruba
 
Àyàfi àwọn olùkírun,

Ayah  70:23  الأية
الَّذِينَ هُمْ عَلَىٰ صَلَاتِهِمْ دَائِمُونَ
Allatheena hum AAala salatihimda-imoon

Yoruba
 
Àwọn tí wọ́n dúnnímọ́ ìrun wọn;

Ayah  70:24  الأية
وَالَّذِينَ فِي أَمْوَالِهِمْ حَقٌّ مَّعْلُومٌ
Wallatheena fee amwalihimhaqqun maAAloom

Yoruba
 
Àwọn tó mọ ojúṣe (wọn) nínú dúkìá wọn

Ayah  70:25  الأية
لِّلسَّائِلِ وَالْمَحْرُومِ
Lissa-ili walmahroom

Yoruba
 
Sí alágbe àti ẹni tí A ṣe arísìkí ní èèwọ̀ fún;

Ayah  70:26  الأية
وَالَّذِينَ يُصَدِّقُونَ بِيَوْمِ الدِّينِ
Wallatheena yusaddiqoonabiyawmi addeen

Yoruba
 
Àwọn tó ń gba ọjọ́ ẹ̀san gbọ́ ní òdodo;

Ayah  70:27  الأية
وَالَّذِينَ هُم مِّنْ عَذَابِ رَبِّهِم مُّشْفِقُونَ
Wallatheena hum min AAathabirabbihim mushfiqoon

Yoruba
 
Àwọn tó ń páyà ìyà Olúwa wọn,

Ayah  70:28  الأية
إِنَّ عَذَابَ رَبِّهِمْ غَيْرُ مَأْمُونٍ
Inna AAathaba rabbihim ghayru ma/moon

Yoruba
 
Dájúdájú ìyà Olúwa wọn kò ṣeé fàyàbalẹ̀ sí;

Ayah  70:29  الأية
وَالَّذِينَ هُمْ لِفُرُوجِهِمْ حَافِظُونَ
Wallatheena hum lifuroojihim hafithoon

Yoruba
 
Àwọn tó ń ṣọ́ abẹ́ wọn,

Ayah  70:30  الأية
إِلَّا عَلَىٰ أَزْوَاجِهِمْ أَوْ مَا مَلَكَتْ أَيْمَانُهُمْ فَإِنَّهُمْ غَيْرُ مَلُومِينَ
Illa AAala azwajihim awma malakat aymanuhum fa-innahum ghayru maloomeen

Yoruba
 
Àyàfi lọ́dọ̀ àwọn ìyàwó wọn tàbí ẹrúbìnrin wọn ni wọn kò ti lè jẹ́ ẹni-èébú,

Ayah  70:31  الأية
فَمَنِ ابْتَغَىٰ وَرَاءَ ذَٰلِكَ فَأُولَٰئِكَ هُمُ الْعَادُونَ
Famani ibtagha waraa thalikafaola-ika humu alAAadoon

Yoruba
 
Nítorí náà, ẹnikẹ́ni tó bá ń wá n̄ǹkan mìíràn lẹ́yìn ìyẹn, àwọn wọ̀nyẹn gan-an ni olùtayọ-ẹnu ààlà;

Ayah  70:32  الأية
وَالَّذِينَ هُمْ لِأَمَانَاتِهِمْ وَعَهْدِهِمْ رَاعُونَ
Wallatheena hum li-amanatihimwaAAahdihim raAAoon

Yoruba
 
Àwọn tó ń ṣọ́ àgbàfipamọ́ wọn àti àdéhùn wọn;

Ayah  70:33  الأية
وَالَّذِينَ هُم بِشَهَادَاتِهِمْ قَائِمُونَ
Wallatheena hum bishahadatihimqa-imoon

Yoruba
 
Àwọn tó ń dúró ti ìjẹ́rìí (òdodo) wọn;

Ayah  70:34  الأية
وَالَّذِينَ هُمْ عَلَىٰ صَلَاتِهِمْ يُحَافِظُونَ
Wallatheena hum AAala salatihimyuhafithoon

Yoruba
 
Àti àwọn tó ń ṣọ́ àwọn ìrun wọn.

Ayah  70:35  الأية
أُولَٰئِكَ فِي جَنَّاتٍ مُّكْرَمُونَ
Ola-ika fee jannatin mukramoon

Yoruba
 
Àwọn wọ̀nyẹn ni alápọ̀n-ọ́nlé nínú àwọn Ọgbà Ìdẹ̀ra.

Ayah  70:36  الأية
فَمَالِ الَّذِينَ كَفَرُوا قِبَلَكَ مُهْطِعِينَ
Famali allatheena kafarooqibalaka muhtiAAeen

Yoruba
 
Kí ló mú àwọn tí kò gbàgbọ́ tí ara wọn kò balẹ̀ níwájú rẹ,

Ayah  70:37  الأية
عَنِ الْيَمِينِ وَعَنِ الشِّمَالِ عِزِينَ
AAani alyameeni waAAani ashshimaliAAizeen

Yoruba
 
Tí wọ́n sì jókòó ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí sí ọwọ́ ọ̀tún àti ọwọ́ òsì (rẹ)?

Ayah  70:38  الأية
أَيَطْمَعُ كُلُّ امْرِئٍ مِّنْهُمْ أَن يُدْخَلَ جَنَّةَ نَعِيمٍ
AyatmaAAu kullu imri-in minhum anyudkhala jannata naAAeem

Yoruba
 
Ṣé ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú wọn ń jẹ̀rankàn pé A óò mú òun wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra ni?

Ayah  70:39  الأية
كَلَّا ۖ إِنَّا خَلَقْنَاهُم مِّمَّا يَعْلَمُونَ
Kalla inna khalaqnahummimma yaAAlamoon

Yoruba
 
Rárá o! Dájúdájú Àwa ṣẹ̀dá wọn láti inú ohun tí wọ́n mọ̀.

Ayah  70:40  الأية
فَلَا أُقْسِمُ بِرَبِّ الْمَشَارِقِ وَالْمَغَارِبِ إِنَّا لَقَادِرُونَ
Fala oqsimu birabbi almashariqiwalmagharibi inna laqadiroon

Yoruba
 
Nítorí náà, Èmi ń fi Olúwa àwọn ibùyọ òòrùn àti àwọn ibùwọ̀ òòrùn búra, dájúdájú Àwa ni Alágbára

Ayah  70:41  الأية
عَلَىٰ أَن نُّبَدِّلَ خَيْرًا مِّنْهُمْ وَمَا نَحْنُ بِمَسْبُوقِينَ
AAala an nubaddila khayran minhum wamanahnu bimasbooqeen

Yoruba
 
Láti yí (ìrísí wọn) padà (ní ọjọ́ Àjíǹde) sí (ìrísí kan) tó máa dára ju (ìrísí) wọn (tayé). Kò sì sí ẹni tó lè dá Wa lágara.

Ayah  70:42  الأية
فَذَرْهُمْ يَخُوضُوا وَيَلْعَبُوا حَتَّىٰ يُلَاقُوا يَوْمَهُمُ الَّذِي يُوعَدُونَ
Fatharhum yakhoodoowayalAAaboo hatta yulaqoo yawmahumu allatheeyooAAadoon

Yoruba
 
Nítorí náà, fi wọ́n sílẹ̀ kí wọ́n máa sọ ìsọkúsọ (wọn), kí wọ́n sì máa ṣeré títí wọn yóò fi pàdé ọjọ́ wọn tí À ń ṣe ní àdéhùn fún wọn.

Ayah  70:43  الأية
يَوْمَ يَخْرُجُونَ مِنَ الْأَجْدَاثِ سِرَاعًا كَأَنَّهُمْ إِلَىٰ نُصُبٍ يُوفِضُونَ
Yawma yakhrujoona mina al-ajdathi siraAAankaannahum ila nusubin yoofidoon

Yoruba
 
Ọjọ́ tí wọn yóò sáré jáde wéréwéré láti inú àwọn sàréè, wọn yó sì dà bí ẹni pé wọ́n ń yára lọ sídìí ohun àfojúsùn kan.

Ayah  70:44  الأية
خَاشِعَةً أَبْصَارُهُمْ تَرْهَقُهُمْ ذِلَّةٌ ۚ ذَٰلِكَ الْيَوْمُ الَّذِي كَانُوا يُوعَدُونَ
KhashiAAatan absaruhumtarhaquhum thillatun thalika alyawmu allatheekanoo yooAAadoon

Yoruba
 
Ojú wọn yóò wálẹ̀. Ìyẹpẹrẹ máa bò wọ́n mọ́lẹ̀. Ọjọ́ yẹn ni èyí tí À ń ṣe ní àdéhùn fún wọn.





© EsinIslam.Com Designed & produced by The Awqaf London. Please pray for us