1st Ayah 1 الأية ١الأوليبِسْم ِ اللهِ الرَّحْمَٰنِ الرَّحِيمِ
الْحَاقَّةُ
Alhaqqa
Yoruba
Ìṣẹ̀lẹ̀ Òdodo náà!
|
Ayah 69:2 الأية
مَا الْحَاقَّةُ
Ma alhaqqa
Yoruba
Kí ni Ìṣẹ̀lẹ̀ Òdodo náà?
|
Ayah 69:3 الأية
وَمَا أَدْرَاكَ مَا الْحَاقَّةُ
Wama adraka ma alhaqqa
Yoruba
Kí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Ìṣẹ̀lẹ̀ Òdodo náà?
|
Ayah 69:4 الأية
كَذَّبَتْ ثَمُودُ وَعَادٌ بِالْقَارِعَةِ
Kaththabat thamoodu waAAadun bilqariAAa
Yoruba
Àwọn ìjọ Thamūd àti ìjọ ‘Ād pe Àjíǹde (ajámọláya bí àrá) ní irọ́.
|
Ayah 69:5 الأية
فَأَمَّا ثَمُودُ فَأُهْلِكُوا بِالطَّاغِيَةِ
Faamma thamoodu faohlikoo bittaghiya
Yoruba
Ní ti ìjọ Thamūd, wọ́n fi igbe tó tayọ ẹnu-ààlà pa wọ́n rẹ́.
|
Ayah 69:6 الأية
وَأَمَّا عَادٌ فَأُهْلِكُوا بِرِيحٍ صَرْصَرٍ عَاتِيَةٍ
Waamma AAadun faohlikoo bireehinsarsarin AAatiya
Yoruba
Ní ti ìjọ ‘Ād, wọ́n fi atẹ́gùn líle tó tayọ ẹnu-ààlà pa wọ́n rẹ́.
|
Ayah 69:7 الأية
سَخَّرَهَا عَلَيْهِمْ سَبْعَ لَيَالٍ وَثَمَانِيَةَ أَيَّامٍ حُسُومًا فَتَرَى
الْقَوْمَ فِيهَا صَرْعَىٰ كَأَنَّهُمْ أَعْجَازُ نَخْلٍ خَاوِيَةٍ
Sakhkharaha AAalayhim sabAAa layalinwathamaniyata ayyamin husooman fataraalqawma
feeha sarAAa kaannahum aAAjazunakhlin khawiya
Yoruba
Ó dẹ ẹ́ sí wọn fún òru méje àti ọ̀sán mẹ́jọ láì dáwọ́ dúró. O sì máa rí ìjọ náà tí wọ́n ti kú sínú rẹ̀ bí ẹni pé kùkùté igi dàbínù tó ti luhò nínú ni wọ́n.
|
Ayah 69:8 الأية
فَهَلْ تَرَىٰ لَهُم مِّن بَاقِيَةٍ
Fahal tara lahum min baqiya
Yoruba
Ǹjẹ́ o rí ẹnì kan nínú wọn tó ṣẹ́ kù bí?
|
Ayah 69:9 الأية
وَجَاءَ فِرْعَوْنُ وَمَن قَبْلَهُ وَالْمُؤْتَفِكَاتُ بِالْخَاطِئَةِ
Wajaa firAAawnu waman qablahu walmu/tafikatubilkhati-a
Yoruba
Fir‘aon àti àwọn tó ṣíwájú rẹ̀ àti àwọn ìlú tí wọ́n dojú rẹ̀ bolẹ̀ dé pẹ̀lú àwọn àṣìṣe.
|
Ayah 69:10 الأية
فَعَصَوْا رَسُولَ رَبِّهِمْ فَأَخَذَهُمْ أَخْذَةً رَّابِيَةً
FaAAasaw rasoola rabbihim faakhathahumakhthatan rabiya
Yoruba
Wọ́n yapa Òjíṣẹ́ Olúwa wọn. Ó sì gbá wọn mú ní ìgbámú tóléken̄kà.
|
Ayah 69:11 الأية
إِنَّا لَمَّا طَغَى الْمَاءُ حَمَلْنَاكُمْ فِي الْجَارِيَةِ
Inna lamma taghaalmao hamalnakum fee aljariya
Yoruba
Dájúdájú nígbà tí omi tayọ ẹnu-ààlà. A gbe yín gun ọkọ̀ ojú-omi.
|
Ayah 69:12 الأية
لِنَجْعَلَهَا لَكُمْ تَذْكِرَةً وَتَعِيَهَا أُذُنٌ وَاعِيَةٌ
LinajAAalaha lakum tathkiratanwataAAiyaha othunun waAAiya
Yoruba
Nítorí kí Á lè fi ṣe ìrántí fún yín àti nítorí kí etí tó ń ṣọ́ n̄ǹkan lè ṣọ́ ọ.
|
Ayah 69:13 الأية
فَإِذَا نُفِخَ فِي الصُّورِ نَفْخَةٌ وَاحِدَةٌ
Fa-itha nufikha fee assoorinafkhatun wahida
Yoruba
Nígbà tí wọ́n bá fọn fèrè oníwo fún ikú ní fífọn ẹyọ kan,
|
Ayah 69:14 الأية
وَحُمِلَتِ الْأَرْضُ وَالْجِبَالُ فَدُكَّتَا دَكَّةً وَاحِدَةً
Wahumilati al-ardu waljibalufadukkata dakkatan wahida
Yoruba
Tí wọ́n gbé ilẹ̀ àti àpáta sókè, tí wọ́n sì rún méjèèjì wómúwómú ní rírún ẹ̀ẹ̀ kan,
|
Ayah 69:15 الأية
فَيَوْمَئِذٍ وَقَعَتِ الْوَاقِعَةُ
Fayawma-ithin waqaAAati alwaqiAAa
Yoruba
Ní ọjọ́ yẹn ni Ìṣẹ̀lẹ̀ máa ṣẹlẹ̀.
|
Ayah 69:16 الأية
وَانشَقَّتِ السَّمَاءُ فَهِيَ يَوْمَئِذٍ وَاهِيَةٌ
Wanshaqqati assamaofahiya yawma-ithin wahiya
Yoruba
Àti pé sánmọ̀ yó fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Ó sì máa fúyẹ́ gẹgẹ ní ọjọ́ yẹn.
|
Ayah 69:17 الأية
وَالْمَلَكُ عَلَىٰ أَرْجَائِهَا ۚ وَيَحْمِلُ عَرْشَ رَبِّكَ فَوْقَهُمْ
يَوْمَئِذٍ ثَمَانِيَةٌ
Walmalaku AAala arja-ihawayahmilu AAarsha rabbika fawqahum yawma-ithin thamaniya
Yoruba
Àwọn mọlāika sì máa wà ní àwọn ẹ̀gbẹ́ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àti pé ní ọjọ́ yẹn, lókè̀wọn, àwọn (mọlāika) mẹ́jọ ni wọ́n máa ru Ìtẹ́ Olúwa rẹ.
|
Ayah 69:18 الأية
يَوْمَئِذٍ تُعْرَضُونَ لَا تَخْفَىٰ مِنكُمْ خَافِيَةٌ
Yawma-ithin tuAAradoona latakhfa minkum khafiya
Yoruba
Ní ọjọ́ yẹn, wọn yóò máa ṣẹ́rí yín wá (fún ìṣírò-iṣẹ́). Kò sì níí sí àṣírí yín kan tó máa pamọ́ (fún Wa).
|
Ayah 69:19 الأية
فَأَمَّا مَنْ أُوتِيَ كِتَابَهُ بِيَمِينِهِ فَيَقُولُ هَاؤُمُ اقْرَءُوا
كِتَابِيَهْ
Faamma man ootiya kitabahubiyameenihi fayaqoolu haomu iqraoo kitabiyah
Yoruba
Nítorí náà, ní ti ẹni tí wọ́n bá fún ní tírà rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, ó máa sọ pé: "Ẹ gbà, ẹ ka tírà mi wò.
|
Ayah 69:20 الأية
إِنِّي ظَنَنتُ أَنِّي مُلَاقٍ حِسَابِيَهْ
Innee thanantu annee mulaqinhisabiyah
Yoruba
Dájúdájú èmi ti mọ àmọ̀dájú pé dájúdájú èmi yóò bá ìṣírò-iṣẹ́ mi pàdé."
|
Ayah 69:21 الأية
فَهُوَ فِي عِيشَةٍ رَّاضِيَةٍ
Fahuwa fee AAeeshatin radiya
Yoruba
Nítorí náà, ó máa wà nínú ìṣẹ̀mí tó máa yọ́nú sí
|
Ayah 69:22 الأية
فِي جَنَّةٍ عَالِيَةٍ
Fee jannatin AAaliya
Yoruba
Nínú Ọgbà Ìdẹ̀ra gíga.
|
Ayah 69:23 الأية
قُطُوفُهَا دَانِيَةٌ
Qutoofuha daniya
Yoruba
Àwọn èso rẹ̀ (sì) máa wà ní àrọ́wọ́tó.
|
Ayah 69:24 الأية
كُلُوا وَاشْرَبُوا هَنِيئًا بِمَا أَسْلَفْتُمْ فِي الْأَيَّامِ الْخَالِيَةِ
Kuloo washraboo hanee-an bimaaslaftum fee al-ayyami alkhaliya
Yoruba
Ẹ jẹ, kí ẹ sì mu pẹ̀lú ìgbàdún nítorí ohun tí ẹ tì síwájú nínú àwọn ọjọ́ tí ó ti ré kọjá.
|
Ayah 69:25 الأية
وَأَمَّا مَنْ أُوتِيَ كِتَابَهُ بِشِمَالِهِ فَيَقُولُ يَا لَيْتَنِي لَمْ أُوتَ
كِتَابِيَهْ
Waamma man ootiya kitabahubishimalihi fayaqoolu ya laytanee lam oota kitabiyah
Yoruba
Ní ti ẹni tí wọ́n bá sì fún ní tírà rẹ̀ ní ọwọ́ òsì rẹ̀, ó máa wí pé: "Háà! Kí wọ́n sì má fún mi ni tírà mi!
|
Ayah 69:26 الأية
وَلَمْ أَدْرِ مَا حِسَابِيَهْ
Walam adri ma hisabiyah
Yoruba
Àti pé kí èmi sì má mọ ohun tí ìṣírò-iṣẹ́ mi jẹ́.
|
Ayah 69:27 الأية
يَا لَيْتَهَا كَانَتِ الْقَاضِيَةَ
Ya laytaha kanati alqadiya
Yoruba
Háà! Kí ikú sì jẹ́ òpin (ọ̀rọ̀ ẹ̀dá).
|
Ayah 69:28 الأية
مَا أَغْنَىٰ عَنِّي مَالِيَهْ ۜ
Ma aghna AAannee maliyah
Yoruba
Dúkìá mi kò sì rọ̀ mí lọ́rọ̀.
|
Ayah 69:29 الأية
هَلَكَ عَنِّي سُلْطَانِيَهْ
Halaka AAannee sultaniyah
Yoruba
Agbára mi sì ti parun."
|
Ayah 69:30 الأية
خُذُوهُ فَغُلُّوهُ
Khuthoohu faghullooh
Yoruba
Ẹ mú un, kí ẹ dè é ní ọwọ́ mọ́ ọrùn.
|
Ayah 69:31 الأية
ثُمَّ الْجَحِيمَ صَلُّوهُ
Thumma aljaheema sallooh
Yoruba
Lẹ́yìn náà, inú iná Jẹhīm ni kí ẹ mú un wọ̀.
|
Ayah 69:32 الأية
ثُمَّ فِي سِلْسِلَةٍ ذَرْعُهَا سَبْعُونَ ذِرَاعًا فَاسْلُكُوهُ
Thumma fee silsilatin tharAAuhasabAAoona thiraAAan faslukooh
Yoruba
Lẹ́yìn náà, inú ẹ̀wọ̀n tí gígùn rẹ̀ jẹ́ àádọ́rin gígùn thar‘u ni kí ẹ kì í sí.
|
Ayah 69:33 الأية
إِنَّهُ كَانَ لَا يُؤْمِنُ بِاللهِ الْعَظِيمِ
Innahu kana la yu/minu billahialAAatheem
Yoruba
Dájúdájú òun kì í gbàgbọ́ nínú Allāhu, Atóbi.
|
Ayah 69:34 الأية
وَلَا يَحُضُّ عَلَىٰ طَعَامِ الْمِسْكِينِ
Wala yahuddu AAalataAAami almiskeen
Yoruba
Kì í sì gba ènìyàn níyànjú láti bọ́ àwọn mẹ̀kúnnù.
|
Ayah 69:35 الأية
فَلَيْسَ لَهُ الْيَوْمَ هَاهُنَا حَمِيمٌ
Falaysa lahu alyawma hahuna hameem
Yoruba
Nítorí náà, kò níí sí ọ̀rẹ́ ìmùlẹ̀ kan fún un níbí yìí ní òní.
|
Ayah 69:36 الأية
وَلَا طَعَامٌ إِلَّا مِنْ غِسْلِينٍ
Wala taAAamun illamin ghisleen
Yoruba
Kò sì níí sí oúnjẹ kan (fún un) bí kò ṣe (oúnjẹ) àwọnúwẹ̀jẹ̀.
|
Ayah 69:37 الأية
لَّا يَأْكُلُهُ إِلَّا الْخَاطِئُونَ
La ya/kuluhu illa alkhati-oon
Yoruba
Kò sí ẹni tí ó máa jẹ ẹ́ bí kò ṣe àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.
|
Ayah 69:38 الأية
فَلَا أُقْسِمُ بِمَا تُبْصِرُونَ
Fala oqsimu bima tubsiroon
Yoruba
Nítorí náà, Èmi ń fi ohun tí ẹ̀ ń fojú rí búra
|
Ayah 69:39 الأية
وَمَا لَا تُبْصِرُونَ
Wama la tubsiroon
Yoruba
Àti ohun tí ẹ ò fojú rí.
|
Ayah 69:40 الأية
إِنَّهُ لَقَوْلُ رَسُولٍ كَرِيمٍ
Innahu laqawlu rasoolin kareem
Yoruba
Dájúdájú al-Ƙur'ān ni ọ̀rọ̀ (tí A fi rán) Òjíṣẹ́, alápọ̀n-ọ́nlé.
|
Ayah 69:41 الأية
وَمَا هُوَ بِقَوْلِ شَاعِرٍ ۚ قَلِيلًا مَّا تُؤْمِنُونَ
Wama huwa biqawli shaAAirinqaleelan ma tu/minoon
Yoruba
Kì í ṣe ọ̀rọ̀ eléwì. Ohun tí ẹ gbàgbọ́ kéré púpọ̀.
|
Ayah 69:42 الأية
وَلَا بِقَوْلِ كَاهِنٍ ۚ قَلِيلًا مَّا تَذَكَّرُونَ
Wala biqawli kahinin qaleelanma tathakkaroon
Yoruba
Kì í sì ṣe ọ̀rọ̀ adábigba. Díẹ̀ lẹ̀ ń lò nínú ìrántí.
|
Ayah 69:43 الأية
تَنزِيلٌ مِّن رَّبِّ الْعَالَمِينَ
Tanzeelun min rabbi alAAalameen
Yoruba
Wọ́n sọ̀ ọ́ kalẹ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
|
Ayah 69:44 الأية
وَلَوْ تَقَوَّلَ عَلَيْنَا بَعْضَ الْأَقَاوِيلِ
Walaw taqawwala AAalayna baAAdaal-aqaweel
Yoruba
Tí ó bá jẹ́ pé (Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - ) dá àdápa apá kan ọ̀rọ̀ náà mọ́ Wa ni,
|
Ayah 69:45 الأية
لَأَخَذْنَا مِنْهُ بِالْيَمِينِ
Àwa ìbá gbá a mú lọ́wọ́ ọ̀tún.
Yoruba
Àwa ìbá gbá a mú lọ́wọ́ ọ̀tún.
|
Ayah 69:46 الأية
ثُمَّ لَقَطَعْنَا مِنْهُ الْوَتِينَ
Thumma laqataAAna minhualwateen
Yoruba
Lẹ́yìn náà, Àwa ìbá já isan ọrùn rẹ̀.
|
Ayah 69:47 الأية
فَمَا مِنكُم مِّنْ أَحَدٍ عَنْهُ حَاجِزِينَ
Fama minkum min ahadin AAanhu hajizeen
Yoruba
Kò sì sí ẹnì kan nínú yín tí ó máa gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ (Wa).
|
Ayah 69:48 الأية
وَإِنَّهُ لَتَذْكِرَةٌ لِّلْمُتَّقِينَ
Wa-innahu latathkiratun lilmuttaqeen
Yoruba
Dájúdájú (al-Ƙur'ān) ni ìrántí fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).
|
Ayah 69:49 الأية
وَإِنَّا لَنَعْلَمُ أَنَّ مِنكُم مُّكَذِّبِينَ
Wa-inna lanaAAlamu anna minkum mukaththibeen
Yoruba
Dájúdájú Àwa sì mọ̀ pé àwọn tó ń pe al-Ƙur'ān ní irọ́ wà nínú yín.
|
Ayah 69:50 الأية
وَإِنَّهُ لَحَسْرَةٌ عَلَى الْكَافِرِينَ
Wa-innahu lahasratun AAala alkafireen
Yoruba
Dájúdájú al-Ƙur'ān máa jẹ́ àbámọ̀ ńlá fún àwọn aláìgbàgbọ́.
|
Ayah 69:51 الأية
وَإِنَّهُ لَحَقُّ الْيَقِينِ
Wa-innahu lahaqqu alyaqeen
Yoruba
Dájúdájú al-Ƙur'ān ni òdodo tó dájú.
|
Ayah 69:52 الأية
فَسَبِّحْ بِاسْمِ رَبِّكَ الْعَظِيمِ
Fasabbih bismi rabbika alAAatheem
Yoruba
Nítorí náà, ṣàfọ̀mọ́ fún orúkọ Olúwa Rẹ, Atóbi.
|
|